ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 17:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Jèhófà lo gbogbo wòlíì rẹ̀ àti gbogbo aríran+ rẹ̀ láti máa kìlọ̀ fún Ísírẹ́lì àti Júdà pé: “Ẹ kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú yín!+ Kí ẹ máa pa àwọn àṣẹ mi àti àwọn ìlànà mi mọ́, bó ṣe wà nínú gbogbo òfin tí mo pa láṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, tí mo sì fi rán àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín.”

  • Àìsáyà 55:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 Kí èèyàn burúkú fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀,+

      Kí ẹni ibi sì yí èrò rẹ̀ pa dà;

      Kó pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà, ẹni tó máa ṣàánú rẹ̀,+

      Sọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, torí ó máa dárí jini fàlàlà.*+

  • Jeremáyà 18:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 “Ní báyìí, jọ̀wọ́ sọ fún àwọn èèyàn Júdà àti àwọn tó ń gbé ní Jerúsálẹ́mù pé, ‘Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Wò ó, mò ń ṣètò àjálù kan fún yín, mo sì ń pète ohun kan fún yín. Torí náà, ẹ jọ̀wọ́, ẹ yí pa dà kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ọ̀nà yín àti ìwà yín ṣe.”’”+

  • Jeremáyà 35:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Mo sì ń rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín, mò ń rán wọn léraléra,*+ wọ́n ń sọ pé, ‘Ẹ jọ̀wọ́, ẹ yí pa dà, kí kálukú yín kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀,+ kí ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́! Ẹ má ṣe tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì, ẹ má sì sìn wọ́n. Nígbà náà, ẹ ó máa gbé ní ilẹ̀ tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba ńlá yín.’+ Ṣùgbọ́n ẹ kò dẹ etí yín sílẹ̀, ẹ kò sì fetí sí mi.

  • Ìsíkíẹ́lì 18:30
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 30 “‘Torí náà, màá fi ìwà yín dá kálukú yín lẹ́jọ́,+ ilé Ísírẹ́lì,’ ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí. ‘Ẹ yí pa dà, àní ẹ yí pa dà pátápátá kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí wọ́n má bàa di ohun ìkọ̀sẹ̀ tó máa mú kí ẹ jẹ̀bi.

  • Ìsíkíẹ́lì 33:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Sọ fún wọn pé, ‘“Bí mo ti wà láàyè,” ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí, “inú mi ò dùn sí ikú ẹni burúkú,+ bí kò ṣe pé kí ẹni burúkú yí ìwà rẹ̀ pa dà,+ kó sì máa wà láàyè.+ Ẹ yí pa dà, ẹ yí ìwà búburú yín pa dà,+ ṣé ó wá yẹ kí ẹ kú ni, ilé Ísírẹ́lì?”’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́