Àìsáyà 51:3 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 3 Torí Jèhófà máa tu Síónì nínú.+ Ó máa tu gbogbo àwókù rẹ̀ nínú,+Ó máa mú kí aginjù rẹ̀ rí bí Édẹ́nì,+Ó sì máa mú kí aṣálẹ̀ rẹ̀ tó tẹ́jú rí bí ọgbà Jèhófà.+ Ìdùnnú àti ayọ̀ máa wà níbẹ̀,Ìdúpẹ́ àti orin tó dùn.+ Jeremáyà 30:18, 19 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 18 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Wò ó, màá kó àwọn tó lọ sí oko ẹrú láti àgọ́ Jékọ́bù jọ,+Máa sì ṣojú àánú sí àwọn àgọ́ ìjọsìn rẹ̀. Wọ́n á tún ìlú náà kọ́ sórí òkìtì rẹ̀,+Ibi tó sì yẹ ni wọ́n á kọ́ ilé gogoro rẹ̀ tó láàbò sí. 19 Ìdúpẹ́ àti ohùn ẹ̀rín á ti ọ̀dọ̀ wọn wá.+ Màá sọ wọ́n di púpọ̀, wọn ò sì ní kéré níye;+Màá mú kí wọ́n pọ̀ níye,*Wọn ò sì ní jẹ́ ẹni yẹpẹrẹ.+ Émọ́sì 9:14 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 14 Màá kó àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì tó wà ní ìgbèkùn pa dà,+Wọ́n á tún àwọn ìlú tó ti di ahoro kọ́, wọ́n á sì máa gbé inú wọn;+Wọ́n á gbin ọgbà àjàrà, wọ́n á sì mu wáìnì wọn,+Wọ́n á ṣe ọgbà, wọ́n á sì jẹ èso wọn.’+
3 Torí Jèhófà máa tu Síónì nínú.+ Ó máa tu gbogbo àwókù rẹ̀ nínú,+Ó máa mú kí aginjù rẹ̀ rí bí Édẹ́nì,+Ó sì máa mú kí aṣálẹ̀ rẹ̀ tó tẹ́jú rí bí ọgbà Jèhófà.+ Ìdùnnú àti ayọ̀ máa wà níbẹ̀,Ìdúpẹ́ àti orin tó dùn.+
18 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Wò ó, màá kó àwọn tó lọ sí oko ẹrú láti àgọ́ Jékọ́bù jọ,+Máa sì ṣojú àánú sí àwọn àgọ́ ìjọsìn rẹ̀. Wọ́n á tún ìlú náà kọ́ sórí òkìtì rẹ̀,+Ibi tó sì yẹ ni wọ́n á kọ́ ilé gogoro rẹ̀ tó láàbò sí. 19 Ìdúpẹ́ àti ohùn ẹ̀rín á ti ọ̀dọ̀ wọn wá.+ Màá sọ wọ́n di púpọ̀, wọn ò sì ní kéré níye;+Màá mú kí wọ́n pọ̀ níye,*Wọn ò sì ní jẹ́ ẹni yẹpẹrẹ.+
14 Màá kó àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì tó wà ní ìgbèkùn pa dà,+Wọ́n á tún àwọn ìlú tó ti di ahoro kọ́, wọ́n á sì máa gbé inú wọn;+Wọ́n á gbin ọgbà àjàrà, wọ́n á sì mu wáìnì wọn,+Wọ́n á ṣe ọgbà, wọ́n á sì jẹ èso wọn.’+