ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 49:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Ọ̀pá àṣẹ kò ní kúrò lọ́dọ̀ Júdà,+ ọ̀pá aláṣẹ kò sì ní kúrò láàárín ẹsẹ̀ rẹ̀ títí Ṣílò* yóò fi dé,+ òun ni àwọn èèyàn yóò máa ṣègbọràn sí.+

  • 1 Àwọn Ọba 8:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Jèhófà ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ, torí mo ti jọba ní ipò Dáfídì bàbá mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Ísírẹ́lì, bí Jèhófà ti ṣèlérí. Mo tún kọ́ ilé kan fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì,+

  • 1 Kíróníkà 17:11-14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 “‘“Nígbà tí o bá kú, tí o sì lọ síbi tí àwọn baba ńlá rẹ wà, màá gbé ọmọ* rẹ dìde lẹ́yìn rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ rẹ,+ màá sì fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀.+ 12 Òun ló máa kọ́ ilé fún mi,+ màá sì fìdí ìtẹ́ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.+ 13 Màá di bàbá rẹ̀, á sì di ọmọ mi.+ Mi ò ní mú ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ kúrò lára rẹ̀+ bí mo ṣe mú un kúrò lára ẹni tó ṣáájú rẹ.+ 14 Màá mú kó dúró nínú ilé mi àti nínú ìjọba mi títí láé,+ ìtẹ́ rẹ̀ á sì wà títí láé.”’”+

  • Sáàmù 132:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Jèhófà ti búra fún Dáfídì,

      Ó dájú pé kò ní ṣàìmú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ pé:

      “Ọ̀kan lára ọmọ* rẹ

      Ni màá gbé gorí ìtẹ́ rẹ.+

  • Àìsáyà 9:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 Àkóso* rẹ̀ á máa gbilẹ̀ títí lọ,

      Àlàáfíà kò sì ní lópin,+

      Lórí ìtẹ́ Dáfídì+ àti lórí ìjọba rẹ̀,

      Kó lè fìdí rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in,+ kó sì gbé e ró,

      Nípasẹ̀ ìdájọ́+ tí ó tọ́ àti òdodo,+

      Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.

      Ìtara Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun máa ṣe èyí.

  • Àìsáyà 11:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Ẹ̀ka igi+ kan máa yọ látinú kùkùté Jésè,+

      Èéhù+ kan látinú gbòǹgbò rẹ̀ sì máa so èso.

  • Mátíù 21:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Bákan náà, àwọn èrò tó ń lọ níwájú rẹ̀ àti àwọn tó ń tẹ̀ lé e ń kígbe ṣáá pé: “A bẹ̀ ọ́, gba Ọmọ Dáfídì là!+ Ìbùkún ni fún ẹni tó ń bọ̀ ní orúkọ Jèhófà!*+ A bẹ̀ ọ́, gbà á là, ní ibi gíga lókè!”+

  • Mátíù 22:42
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 42 “Kí lèrò yín nípa Kristi? Ọmọ ta ni?” Wọ́n sọ fún un pé: “Ọmọ Dáfídì ni.”+

  • Lúùkù 1:32, 33
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 32 Ẹni yìí máa jẹ́ ẹni ńlá,+ wọ́n á máa pè é ní Ọmọ Ẹni Gíga Jù Lọ,+ Jèhófà* Ọlọ́run sì máa fún un ní ìtẹ́ Dáfídì bàbá rẹ̀,+ 33 ó máa jẹ Ọba lórí ilé Jékọ́bù títí láé, Ìjọba rẹ̀ ò sì ní lópin.”+

  • Jòhánù 7:42
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 42 Ṣebí ìwé mímọ́ sọ pé látinú ọmọ Dáfídì ni Kristi ti máa wá,+ ó sì máa wá láti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù,+ abúlé tí Dáfídì wà tẹ́lẹ̀?”+

  • Ìṣe 2:30
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 30 Nítorí pé wòlíì ni, ó sì mọ̀ pé Ọlọ́run ti búra fún òun pé òun máa gbé ọ̀kan lára àwọn ọmọ rẹ̀* gorí ìtẹ́ rẹ̀,+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́