ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 36:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Nítorí náà, ó gbé ọba àwọn ará Kálídíà+ dìde sí wọn, ẹni tó fi idà pa àwọn ọ̀dọ́kùnrin wọn+ nínú ibi mímọ́ wọn;+ kò ṣàánú ọ̀dọ́kùnrin tàbí ọ̀dọ́bìnrin,* arúgbó tàbí aláàárẹ̀.+ Ohun gbogbo ni Ọlọ́run fi lé e lọ́wọ́.+

  • 2 Kíróníkà 36:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Ó sun ilé Ọlọ́run tòótọ́ kanlẹ̀,+ ó wó ògiri Jerúsálẹ́mù lulẹ̀,+ ó sun gbogbo àwọn ilé gogoro tó láàbò, ó sì ba gbogbo ohun tó ṣeyebíye jẹ́.+

  • Jeremáyà 17:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 “‘“Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá ṣègbọràn sí àṣẹ tí mo pa pé kí ẹ jẹ́ kí ọjọ́ Sábáàtì máa jẹ́ mímọ́, tí ẹ̀ ń ru ẹrù, tí ẹ sì ń gbé e gba àwọn ẹnubodè Jerúsálẹ́mù ní ọjọ́ Sábáàtì, ṣe ni màá sọ iná sí àwọn ẹnubodè rẹ̀, ó sì dájú pé á jó àwọn ilé gogoro tó láàbò ní Jerúsálẹ́mù run,+ a kò sì ní pa iná náà.”’”+

  • Jeremáyà 34:2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Lọ bá Sedekáyà+ ọba Júdà sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún un pé: “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Wò ó, màá fi ìlú yìí lé ọwọ́ ọba Bábílónì, á sì dáná sun ún.+

  • Jeremáyà 37:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Kódà bí ẹ bá pa gbogbo ọmọ ogun Kálídíà tó ń bá yín jà, tó sì jẹ́ pé àwọn tó fara pa nìkan ló ṣẹ́ kù, wọ́n ṣì máa wá látinú àgọ́ wọn, wọ́n á sì dáná sun ìlú yìí.”’”+

  • Jeremáyà 39:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Ìgbà náà ni àwọn ará Kálídíà dáná sun ilé* ọba àti ilé àwọn èèyàn náà,+ wọ́n sì wó àwọn odi Jerúsálẹ́mù lulẹ̀.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́